Browsing Category
ÌRÒYÌN ÒSÈLÚ
This is a category for politics news
Ilé Aṣòfin Èkó Dárò Olóògbé Pa Ayọ̀ Adébánjọ Wọ́n Sàpèjúwe Rẹ̀ Gẹ́gẹ́ Bí Akíkanjú
Wọ́n ti ṣàpèjúwe ikú Olóògbé Ayọ̀délé Adébánjọ gẹ́gẹ́ bí àdánù ńlá fún ìran Yorùbá, nítorí pé, gbogbo ìgbésí ayé rẹ̀ ló fi sin ẹ̀yà náà.
Nínú èsì wọn sí ikú Akíkanjú, Olórí Ẹgbẹ́ Afẹ́nifẹ́re náà, Ilé Ìgbìmọ̀ Aṣòfin Ìpínlẹ̀ Èkó…
Ilé Aṣòfin Èkó Rọ Gómìnà Èkó Láti Parí Àwọn Iṣẹ́ Akànṣe Tó Ń Lọ Lọ́wọ́
Ilé Ìgbìmọ̀ Aṣòfin Ìpínlẹ̀ Èkó rọ Gómìnà Sanwo-Olu láti parí àwọn iṣẹ́ àkànṣe tó ń lọ lọ́wọ́, pàápàá iṣẹ́ àkànṣe ojú ọ̀nà márosẹ̀ Bọla Ahmed Tinubu lọ́nà Ìgbogbo Báyékù, tí wọ́n ti pa tì láti ọdún 2017.
Aṣòfin Aró Moshood tó ń…
Atiku Lọ Rí Obasanjọ Ní Abéòkúta Fún Ìpàdé Ìdakọ́nkọ́
Ìgbákejì ààrẹ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà nígbà kan rí, Atiku Abubakar ti lọ rí ààrẹ tẹ́lẹ̀ rí, Olusegun Obasanjo ní ìlú Abeokuta, ìpínlẹ̀ ogun, gúsù ìwọ̀ oòrùn Nàìjíríà .
O dé sí ibugbe Obasanjo ní gbàgede Olusegun Obasanjo…
APC ṣe ìfilọ́lẹ̀ ìgbìmọ̀ ìpolongo fún ìdíje ìpo Gómìnà Chukwuma
Ẹgbẹ́ òṣèlú All Progressives Congress (APC), ní ìpínlẹ̀ Anambra ti ṣe ìfilọ́lẹ̀ gbangba àwọn alákóso ìjọba ìbílẹ̀ fún agbègbè ìjọba àpapọ̀ Àringbùngbùn ti Anambra fún ìpolongo ìdìbò abẹ́lé fún Paul Chukwuma, ní…
Olùdarí Ilé Aṣòfin Èkó Ti Pé Fún Ìfọwọ́sowọ́pọ̀ Láti Fòpin Sí Dídá Abẹ́ Fún Ọmọbìnrin
Olùdarí Ilé Ìgbìmọ̀ Aṣòfin Ìpínlẹ̀ Èkó, Aṣòfin Mojísọ́lá Maranda ti pé fún ìfọwọ́sowọ́pọ̀ láti fòpin sí dídá abẹ́ fún ọmọbìnrin
Nínú ọ̀rọ̀ rẹ̀ nínú ayẹyẹ ìsàmì àyàjọ́ ìfòpinsí Dídá Abẹ́ fún Ọmọbìnrin Lágbàáyé ti ọdún 2025,…
Ilé Aṣòfin Ìpínlẹ̀ Èkó Mọ Rírí Iṣẹ́ Takuntakun Ààrẹ Tinubu Wọ́n Rí i Gẹ́gẹ́ Bí Ibùkún Sí Orílẹ̀-èdè…
Àwọn ọmọ ẹgbẹ́ Ilé Ìgbìmọ̀ Aṣòfin Ìpínlẹ̀ Èkó ti gbóríyìn fún iṣẹ̀ takuntakun Ìjọba Ààrẹ Tinubu lórílẹ̀-èdè yìí, gẹ́gẹ́ bí Ààrẹ tí Ọlọ́run fi bùkún orílẹ̀-èdè Nàìjíríà.
Nígbà tí wọ́n ń jíròrò nínú gbọ̀ngan Ilé Aṣòfin náà…
Aya Ààrẹ Gbè Ọgọ́rùn ún Mílíọ̀nù Kalẹ̀ Fún Àwọn Tó Lùgbàdí Ìjàmbá Ọkọ̀ Agbépo Dikko Tó Bú Gbàmù
Arábìnrin àkọ́kọ́ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà, Oluremi Tinubu ti gbé Ọgọ́rùn ún Mílíọ̀nù fún àwọn to lùgbàdí isẹ̀lẹ̀ Ìjàmbá ọkọ̀ agbépo Dikko tó bú gbàmù láti fi se ìrànlọ́wọ́ fún wọn.
Ó sọ pé, èyí ti òun se jẹ láti fi kún eléyìí ti…
Ìgbésẹ̀ Tó Tọ́ La Gbé Láti Fi Yọ Aṣòfin Ọbasá Nípò Olùdarí Ilé Aṣòfin Èkó Tẹnu Mọ́ Ọn
Àwọn ọmọ ẹgbẹ́ Ilé Ìgbìmọ̀ Aṣòfin Ìpínlẹ̀ Èkó tẹnu mọ́ ọn pé, Ìgbésẹ̀ tó tọ́ ni àwọn fi yọ Olùdarí Ilé Ìgbìmọ̀ Aṣòfin tẹ́lẹ̀, Aṣòfin Mudashiru Ọbasá nípò.
Nínú àtẹ̀jáde wọn lẹ́yìn tí wọ́n fojú hàn ní ilé iṣẹ́ Ẹ̀ṣọ́ Àláàbò Ìjọba…
Alága Gbogbogbò Ẹgbẹ́ Òṣèlú APC Gba Ọmọ Ẹgbẹ́ Tuntun Ogójì Ẹgbẹ̀rún Wọlé Ní Ìpínlẹ̀ Katsina
Alága Gbogbogbò Ẹgbẹ́ Òsèlú APC, All Progressives Congress, Dokita Abdullahi Ganduje, ti gba ọmọ ẹgbẹ́ tuntun tó tó Ogójì Ẹgbẹ̀rún ti wọn sá kúrò látì ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹgbẹ́ òsèlú ní ìpínlẹ̀ Katsina wọlé sínú Ẹgbẹ́ Òsèlú APC.
Ganduje…
Ìjọba Ìpínlẹ̀ Katsina Jẹ́jẹ̀ẹ́ Láti Se Ètò Ìdìbò Ìjọba Ìbílẹ̀ Tí Kò Ní Ẹja-n-bákàn…
Gómìnà Ìpínlẹ Katsina, Dikko Umaru Radda ti ké sí ẹgbẹ́ òsèlú APC àti àwọn alẹ́nulọ́rọ̀ nínú ẹgbẹ́ náà láti pèpè àtìlẹyìn fún ẹgbẹ́ náà lójúnà àti jáwé olúborí nínú ètò ìdìbò ìjọba ìbílẹ̀ tí ó ń…