Take a fresh look at your lifestyle.

Gómìnà ìpínlẹ̀ Eko Sanwo-Olu yan adarí àwọn òṣìṣẹ́ tuntun

Eyitayọ Fauziat Oyetunji

0 253

Babajide Sanwo-Olu ti ìpínlẹ̀ Eko ti buwọ́lu yíyan Ọ̀gbẹ́ni labọde Agoro gẹ́gẹ́ bíi adarí àwọn òṣìṣẹ́ tuntun ẹlẹ́ẹ̀kejìlé-lógún.

Adarí àwọn òṣìṣẹ́ ti o n lọ bayii, Ọgbẹni Hakeem Muri-Okunola, sọ eyi ninu ifiranṣẹ to fi sita pe yoo bẹrẹ iṣẹ lati ọgbọnjọ, ọṣu kẹsan an.

 “ O pa dandan lati mọ pe, adarí àwọn òṣìṣẹ́ tuntun darapọ mọ oṣiṣẹ ijọba ipinlẹ Eko ni ọjọ kinni, oṣu keje 2003 ti o si jẹ pe lati igba naa lo ti n sin ijọba tọkantọkan ki o to gba igbega si ipo Akọwe agba ni ọjọmkẹta, oṣu kẹjọ, 2015.

Ki wọn to yan si ipo yii, Agoro jẹ Akọwe Agba, ti Lands Bureau,”  Muri-Okunola sọ bayii, ti o si wa rọ gbogbo awọn oṣiṣẹ ijọba lati ṣatilẹyin ati fọwọsowọpọ pẹlu adarí àwọn òṣìṣẹ́ tuntun lori iṣagbelarugẹ awọn aṣeyọri ẹni ti o ṣẹṣẹ fipo silẹ.

Nigba ti o wa n gbadura fun adari awọn osiṣẹ tuntun fun ere to pọ ati aṣeyọri lẹnu iṣẹ, awọn oṣiṣẹ oniṣiro wa rọọ lati ṣakiyesi ifiranṣẹ yii ki o si jẹ ki ó de eti gbogbogboo,”  adarí àwọn òṣìṣẹ́ tí ó ń lọ sọ báyìí.

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *

button