Take a fresh look at your lifestyle.

Mínísítà Ìpínlẹ̀ Fún Iṣẹ́ Àti Ìgbanisisẹ́ Ti Kọ̀wé Fipò Sílẹ̀

181

 

Mínísítà Ìpínlẹ̀ fún Iṣẹ́ àti Ìgbanisisẹ́ Nàìjíríà, Nkeiruka Onyejeocha, ti kọ̀wé fipò rẹ silẹ.

Nigbati o kede ifisẹ́silẹ rẹ lori ayelujara “X” rẹ, Minisita naa fi ọpẹ fun Aare Bola Ahmed Tinubu fun anfani lati ṣiṣẹ ninu iṣakoso ijọba rẹ.

O ṣapejuwe ifisilẹ rẹ gẹgẹbi opin pataki kan ninu iṣẹ ijọba rẹ, o si jẹrisi ifaramo rẹ si idagbasoke orilẹ-ede yìí.

“Eyi kii ṣe opin ṣugbọn ibẹrẹ ọ̀tun. Mo fi ara mi jin fún iṣé, lati tẹsiwaju, ati lati kọ Nàìjíríà ti gbogbo wa yẹ si”.

Onyejeocha dupẹ lọwọ Aare fun ohun ti o pe ni igbẹkẹle ati itọsọna rẹ, o ṣe akiyesi pe ṣiṣiṣẹ labẹ Eto Ireti Tuntun ti ijọba jẹ “ọlá ati anfaani”.

O tun fi ọpẹ han si awọn oṣiṣẹ ati oṣiṣẹ ajọ Federal Ministry of Labour and Employment fun itẹramosẹ́ ati imọ-jinlẹ wọn, o sọ pe ifowosowopo wọn ṣe iranlọwọ lati mu awọn eto imulo ti a pinnu lati daabobo ẹtọ awọn oṣiṣẹ, igbelaruge aabo ibi iṣẹ, ati itẹsiwaju anfààní Ìgbanisisẹ́.

Onyejeocha tún dúpẹ́ lọ́wọ́ àwọn ọmọ ẹgbẹ́ rẹ̀ ní Isuikwuato/Umunneochi Federal Constituency fún atìlẹ́yìn àti ìṣírí wọn ní gbogbo ìgbà tí ó wà nípò.

Ó tún sọ ìpinnu rẹ̀ sí ìtèsíwájú iṣẹ́ ìsìn àti ìlọsíwájú orílẹ̀-èdè yii.

A ó rántí pé Ààrẹ Bola Ahmed Tinubu ti pàṣẹ fún gbogbo àwọn tí wọ́n yàn sípò nínú oṣèlú tí wọ́n fẹ́ díje nínú ìdìbò gbogbogbòò ọdún 2027 láti fi ipò sílẹ̀ kí ó tó di ọjọ́ kọkànlélọ́gbọ̀n oṣù kẹta, ọdún 2026, láti rí i dájú pé gbogbo wọn wà ní ipò tó tọ́.

 

Temitọ́pè Òbísẹ̀san

Comments are closed.

button