Ìjọba Nàìjíríà sọ pé orílẹ̀-èdè ti ṣetán láti di ibùdó-àjò fún àwọn tó ń lọ sí òkèèrè fún ìtọ́jú ara.
Minisita fun Alaye ati Aṣa, Alhaji Lai Mohammed ṣe afihan eyi ni ọjọ iṣẹgun nigba ti o bẹrẹ irin-ajo lọ si ile-iwosan Duchess International Hospital ti o wa ni Ikẹja,ni ilu-Eko,guusu iwọ oorun, Naijiria.
Nipa ṣiṣe bẹẹ, aṣa irin-ajo fun itọju ara yoo dinku ni Naijiria.
Lọwọlọwọ bayii, awọn aririn ajo fun itọju ara lati ọpọlọpọ apakan Iha Iwọ-oorun Sahara ti Adulawọ ti n wa gba itọju ara nibẹ.
Minisita naa sọ pe awọn iṣẹ ti ile-iwosan naa yoo maaṣe yoo din ẹẹdẹgbẹta biliọnu naira ti awọn ọmọ orilẹ-ede Naijiria n na lori irin-ajo itọju ara ku ni ọdọọdun,igbesẹ ti yoo tọju ifiṣura ajeji ati alekun owo ilẹ okeere.
Oye ile-iwosan Duchess International ni lati mu itọju ilera agbaye todangajia ni iwọn owo ti ko jara lọ.
Leave a Reply