Ààrẹ orílẹ̀ èdè Nàíjíríà , Muhammadu Buhari ti korò ojú sí bí àwọn ọ̀daràn se ń pa àwọn ọmọ orílẹ̀ èdè Nàíjíríà, bí eku pàápàá jùlọ ní àwọn ìpínlẹ̀ Zamfara àti Kaduna
Aarẹ Buhari wa tun rọ awọn ile-isẹ ọmọ ogun ati ajọ eleto aabo lorilẹ ede Naijiria, ki wọn tun fún sòkòtò wọn le lati yanju isoro eto aabo to n dojukọ awọn ipinlẹ kan lorilẹ ede yii.
Aarẹ Buhari wa tun koro oju si awọn oloselu kan ti wọn n sọ ọrọ kùnbá-kùngbé lori eto aabo , o wa rọ wọn lati darapọ mọ ijoba lọna ati wa ojutuu si isoro to n dojukọ eto aabo lorilẹ ede yii.
Aarẹ wa fi aidunnu rẹ han lori awọn eniyan to ti padanu ẹ̀mí wọn , o wa rọ ajọ eleto aabo lati dena awọn ikọlu to n sẹlẹ lorilẹ ede yii.