Gomina ìpínlẹ̀ Jigawa , Muhammadu Badaru ti gbóríyìn fún ààrẹ orílẹ̀ èdè Nàíjíríà , Muhammadu Buhari fún gudu gudu méje , yàyà mẹ́fà tí ó ń se fún gbogbo ọmọ orílẹ̀ èdè Nàíjíríà,pàápàá jùlọ lórí pípèsè àwọn ohun amáyédẹrùn àti àtúnse tó gbóúnjẹ fẹ́gbẹ́ , gbàwobọ̀ lórí ètò ọrọ̀ ajé.
Gomina sọrọ yii nibi ayẹyẹ ti wọn se lati fi ki asofin Bent (PDP – Ila Gusu Adamawa ),kaabọ sinu ẹgbẹ oselu All Progressives Congress (APC) lọjọ Abamẹta ni ilu Yola.
Asofin Bent fi ẹgbẹ oselu PDP silẹ lati darapọ mọ ẹgbẹ oselu APC, o tun jẹ ọkan lara igbimọ alakoso fun ẹgbẹ oselu PDP (BOT) ki o to darapọ mọ ẹgbẹ oselu APC. Bakan naa ni Bent tun ti se asoju fun ẹkun ila Gusu ni ipinlẹ Adamawa nile igbimọ asoju sofin laarin ọdun 2007 si 2011.
Badaru ni ijọba aarẹ Buhari ti se aseyege ti alakan n sepo paapaa julọ lori idagbasoke ti o ti mu ba awọn nnkan amayedẹrun bii oju irin, ina mọna-mọna , papa ọkọ oju ofurufu ati idagbasoke to ti mu ba tẹru-tọmọ lorilẹ ede Naijiria.Idi niyi ti awọn kan se n fi .egbẹ oselu wọn silẹ lati darapọ mọ ẹgbẹ oselu APC
Gomina ipinlẹ Yobe ti o tun jẹ adele alaga fun igbimọ to n samojuto ilana ẹgbẹ oselu APC naa tun ki asofin Bent kaabọ sinu ẹgbẹ oselu APC.
Buni, ti o soju fun adari ile igbimọ asofin tẹlẹri , Ken Nnamani wa sọ fun Bent pe ẹgbẹ osleu APC ko ni fi silẹ ninu awọn ipinnu ti wọn yoo maa se nipa ẹgbẹ wọn.
Ọjọgbọn Tahir Mamman, ti o jẹ ọkan pataki ninu ẹgbẹ oselu APC naa wa rọ gbogbo ọmọ ẹgbẹ oselu APC lati wa ni ọkan , ki wọn si fọwọsowọpọ, ki ẹgbẹ oselu APC tun lee jawe olubori ninu eto idibo to tun n bọ.
Leave a Reply