Take a fresh look at your lifestyle.

Mínísítà Uganda Kan B’ẹnú Àtẹ Lú Ìkọlù Àwọn Ológun Kan ‎

212

Mínísítà Ìròyìn Uganda, Chris Baryomunsi, tí b’ẹnú àtẹ lù ìkọlù àwọn ológun sí ilé alátakò ìjọba Bobi Wine ní oṣù tó kọjá.

‎ Ó sọ pé olóṣèlú olórin tẹ́lẹ̀ náà kò dá ẹ̀ṣẹ̀ kankan, ó sì ní òmìnira láti padà síbẹ̀.

‎Wine ti sá sí ìpamọ́ fún ọ̀sẹ̀ mélòó kan lẹ́yìn tó sá kúrò nílé rẹ̀ ní olú-ìlú Kampala, ní wákàtí díẹ̀ kí wọ́n tó kéde pé òun ló gba ipò kejì sí Ààrẹ Yoweri Museveni nínú ìdìbò Ààrẹ ọjọ́ kẹẹ̀ẹ́dógún oṣù kìíní.

‎Ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù kìíní, Wine sọ pé òún ti gbé ìyàwó òun lọ sí ilé ìwòsàn lẹ́yìn tí àwọn ológun ti wọ ilé wọn, Ó sọ pé wọ́n bọ́ aṣọ wọn, wọ́n sì fún un ìyàwó òun ní ọrùn mọlẹ.

‎ Olórí ológun Uganda, Muhoozi Kainerugaba, tó tún jẹ́ ọmọ Museveni, sọ pé àwọn ológun kò fiya jẹ́ ìyàwó Wine, ṣùgbọ́n nígbà tó yá ó sọ ní orí opo X pé àwọn ti “mú un Ìyàwó Wine, lẹ́yìn náà wọ́n sì ti tú u sílẹ̀.”

Baryomunsi, ẹni tó tún jẹ́ agbẹnusọ fún ìjọba, sọ pé àwọn aláṣẹ yóò ṣe ìwádìí lórí ìṣẹ̀lẹ̀ náà.

Comments are closed.

button