Ààrẹ Bola Tinubu tí pàṣẹ fún àwọn élétó ààbò lórílẹ̀-èdè Nàìjíríà láti pèsè ààbò tó péye fún àwọn aráàlú ní gbogbo àgbègbè lórílẹ̀-èdè yìí.
Ààrẹ pàṣẹ fún àwọn élétó ààbò ní Ọjọ́rú nígbàtí Ó ṣé ìpàdé pẹ̀lú àwọn alákóso ààbò náà ní ilé-iṣẹ́ Ààrẹ, Abuja.
Ọgá àgbà àwọn ọmọ ogún Orílẹ̀-èdè yìí Lucky Irabor, sọ pé wọ́n yóò ṣé gbogbo òun tí Ààrẹ fẹ́ ní ìbámu pẹ̀lú ìlànà. Ó sọ èyí dì mímọ Nígbàtí o ń bá àwọn oníròyìn Ilé-iṣẹ́ Ààrẹ sọrọ ní ìparí ìpàdé náà.
O sọ pé àwọn alákóso ààbò ṣe àlàyé fún Ààrẹ lórí ipò ààbò ní gbogbo àgbègbè orílẹ̀-èdè yìí atí káàkiri àgbáyé.

Olùdámọ̀ràn ààbò lórílẹ̀-èdè náà, Major General Babagana Monguno, tí ó ti fẹ̀yìn tì, tún bá àwọn akọ̀ròyìn sọ̀rọ̀.
Tún kà nípa:Ààrẹ Tinubu Ń Ṣé Ìpàdé Pẹ̀lú Àwon Olórí Ààbò
Monguno sọ pé Ààrẹ mọ́ rírí àwọn irúbọ tí àwọn ológun àti àwọn ilé-iṣẹ́ ààbò mìíràn tí ṣé sí ààbò orílẹ̀-èdè náà.
Leave a Reply