Take a fresh look at your lifestyle.

Báńkì fún Iṣẹ́ Àgbẹ̀ Gbóríyìn fún Ìgbìyànjú Ìyàwó Àkọ́kọ́ Lórí Oúnjẹ Tí Kò Péye

68

Olùdarí Àgbà fún Báńkì fún Iṣẹ́ Àgbẹ̀, Ayo Sotinrin ti gbóríyìn fún àwọn ètò iṣẹ́ àgbẹ̀ àti oúnjẹ tí Ìyàwó Àkọ́kọ́ ní Nàìjíríà, Sẹ́nétọ̀ Oluremi Tinubu, ṣe, ó sì ṣàpèjúwe wọn gẹ́gẹ́ bí àwọn ìgbòkègbodò tó lágbára tó ń mú ààbò oúnjẹ lágbára sii àti tó ń kojú ounjẹ ti kò péye àwọn ọmọdé ní orílẹ̀-èdè yìí.

Sótinrin sọ ọ̀rọ̀ yìí nígbà tí Ìyàwó Àkọ́kọ́ gbà á lalejo ní ọ́fíìsì rẹ̀ ní gbọ̀ngán ààrẹ, Abuja.

Sótinrin tẹnu mọ́ ìfilọ́lẹ̀ Ètò apapọ̀ Báńkì fún Oúnjẹ Àwùjọ ti tó ń bọ̀, tí Ìyáàfin Tinubu kéde láìpẹ́ yìí, ó sọ pé ètò náà yóò “kojú ounjẹ ti kò péye láti orísun nípa gbígbé iṣẹ́ oúnjẹ tó ní agbára láti orísun lárugẹ.”

Gẹ́gẹ́ bí ó ti sọ, “ìgbòkègbodò náà ni a ṣe láti rí i dájú pé a lè rí oúnjẹ tó ní peye, to sara loore gbà nígbàtí a sì ń mú kí àwọn ètò oúnjẹ tó ní péye láti agbègbè lágbára ní gbogbo orílẹ̀-èdè yii.”

Olùdarí Àgbà ti Bankii  agbẹ̀  sọ pé òun wà ní ọ́fíìsì aya ààrẹ  láti ṣe àgbékalẹ̀ àwọn kúlẹ̀kúlẹ̀ nípa ìgbékalẹ̀ ètò àjọ “National Community Food Bank”.

Ó ní ìrètí pé àwọn ìran ọmọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà tí ń bọ̀ yóò ní ìlera tó péye.

Tèmítọ́pẹ́ Òbísẹ̀san

Comments are closed.

button