Gómìnà Ọṣun buwọ́lu owó oṣù fún àwọn òṣìṣẹ́ ìjọba, àwọn tí ń gba owó ìsinmi
Eyitayọ Fauziat Oyetunji
Gómìnà Ademọla Adeleke ti ìpínlẹ̀ Ọṣun ti buwọ́lu sisan owó oṣù fún àwọn òṣìṣẹ́ ìjọba, àwọn tí ń gba owó ìsinmi gẹ́gẹ́ bíi ìgbésẹ̀ láti dásí ipa ìmúkúrò àdínkù owó orí epo ilẹ̀.
Nini alaye kan ti agbẹnusọ gomina, Malam Ọlawale Rasheed, buwọlu, Adeleke sọ pe iṣe naa jẹ ara ipinnu rẹ si igbe aye rere awọn oṣiṣẹ ati imuṣẹ ipinnu fifunni ni ohun iranwọ lati din ipa ìmúkúrò àdínkù owó orí epo ilẹ̀ ku.
Ibuwọlu naa ti o wa ninu lẹta kan ti wọn pin kaakiri lati ile iṣẹ ijọba ti n mojuto Orisun eniyan ati Ironiyan lagbara, sọ pe awọn oṣiṣẹ yoo gba ẹgbẹrun mẹẹdogun Naira loṣu, ti àwọn tí ń gba owó ìsinmi yoo si gba ẹgbẹrun mẹwaa Naira.
Lẹta naa ti Akọwe pataki ile iṣẹ ijọba naa, Sunday Olugbenga Fadele buwọlu sọ pe owo oṣu naa yoo waye fun oṣu mẹfa, ti yoo si bẹrẹ ni oṣu kejila.
Leave a Reply