Take a fresh look at your lifestyle.

Mínísítà fún ètò ìbáraẹnisọ̀rọ̀ pè fún ìdàgbàsókè orílẹ̀-èdè lẹ́yìn ìdájọ́ ilé-ẹjọ́ tó ga jùlọ

Eyitayọ Fauziat Oyetunji

0 271

Mínísítà Nàìjíríà fún ètò ìbáraẹnisọ̀rọ̀ àti ìfihàn lápapọ̀, Mohammed Idris ti rọ gbogbo ẹgbẹ́ olóṣèlú àti àwọn àgbààgbà ìlú láti mójú kúrò lórí ìdìbò, kí wọn ó sì gbájúmọ́ bí orílẹ̀-èdè yóò ṣe dàgbàsókè.

Ninu ọrọ rẹ nibi apejọ awọn akọroyin, ni ọjọ Ẹti, ni Abuja, Minisita sọ bayii “ni bayii ti ifigagbaga ofin lori esi ibo aarẹ ti pari, o ti ya bayii lati parapọ fun idagbasoke, si abala iṣakoso ti ko ni idiwọ.”

Nigba ti o n ba awọn akọroyin sọrọ lori bi o ṣe n lọ lorilẹ-ede, Minisita gba pe eto ọrọ-aje ko ri boṣe yẹ ko ri lagbaaye ti o si pe pe gbogbo eniyan lo nipa ti yoo ko lati koju ipeninija naa.

O tun wa n mu daniloju pe Aarẹ Bọla Ahmed Tinubu ti fi sọ pe oun yoo jẹ aarẹ fun gbogbo ọmọ Naijiria: laibikita agbegbe, ẹya, ẹgbẹn, tabi ẹsin ti eeyan n sin.”

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *

button