Ààrẹ Muhammadu Buhari ti kópa nínú ìdìbò láti yan àwọn Gómìnà ti ọdún 2023.
Ààrẹ dìbò ní ọjọ́ Àbámẹ́ta, ní ibùdó ìdìbò Kofar Baru tí ó jẹ́ ìpín kẹta wọ́ọ̀dù ní ìjọba Ìbílẹ̀ Daura, Ìpínlẹ̀ Katsina.
Ààrẹ, ẹni tí ó kọ́wọ̀ọ́rìn pẹ̀lú àwọn ará ilé rẹ̀ ni wọ́n kọ́kọ́ se àyẹ̀wò fún pẹ̀lú ẹ̀rọ ayẹniwò BVAS, síwájú kí wọ́n tó dìbò.
Àrídájú wà pé ètò ìdìbò ń lọ ní ìrọwọ́-rọsẹ̀ jákè-jádò ìpínlẹ̀ náà, nígbà tí àwọn ẹ̀sọ́ aláàbò sì wà ní ojú ni alákàn fi ń sọ́rí, lójúnà àti pèsè ààbò tí ó péye fún ìkẹ́ṣẹjárí ètò ìdìbò.
Leave a Reply