Take a fresh look at your lifestyle.

Orílẹ̀-èdè Nàìjíríà Gbá Látí Só Ìbáṣepọ̀ Wọ́n Pẹ̀lú Iran Lé dọin-dọin

Ọlálékan Ọ̀rẹ́núgà

1 169

Ààrẹ Muhammadu Buhari tí fí dá Ìgbákejì Ààrẹ orílẹ̀-èdè Iran lójú pé òún ṣetán láti sọ d’ọtun ìbáṣepọ̀ tó wà lọwọ́ pẹ̀lú Orílẹ̀-èdè Iran

Ààrẹ Buhari sọ èyí lásìkò tí Ìgbákejì Ààrẹ orílẹ̀-èdè Iran, Mohsen Mansouri ṣé àbẹwò sí níbí ìpàdé àjọ àpapọ̀ àgbáyé tó ń wáyé ní Doha, Olú-ìlú orílẹ̀-èdè Qatar.

Ààrẹ tún sọ fún àlejò rẹ̀ nípa ìdìbò tó wáyé láìpẹ́ yìí ní orílẹ̀-èdè Nàìjíríà àti bí Ààrẹ titun yóò ṣé gbá ìjọba láàárín oṣù mẹta. O fí kún pé òún lérò wípé àjọṣepọ̀ tó lágbára tí òún tí ṣé láàárín àwọn orílẹ̀-èdè méjèèjì yóò tẹ̀síwájú ní sáà túntún náà.

Tún kà nípa: Nàìjíríà Àtí Íńdíà Ṣe Ìfọwọ́sowọ́pọ̀ Lórí Ìwádìí Ìmọ-jinlẹ̀ Ojú-ọjọ́ Àtí Ìdàgbàsókè

Ìgbákejì Ààrẹ Iran náà sọ pé inú òún dùn láti pàdé pẹ̀lú olórí orílẹ̀-èdè Nàìjíríà, ní òye pé àwọn orílẹ̀-èdè méjèèjì ní láti ṣé ìfọ́wọ́sowọlọ̀ pẹ̀lú bí wọ́n ṣé rọ̀rọ́ ní àwọn ọ̀jọ̀gbọ́n àtí àwọn òun alumọni wọ́n, kí wọ́n sì ṣé ìfọwọ́sowọ́pọ̀ ní àgbègbè mìíràn bí ìṣẹ́ àgbẹ̀.

Leave A Reply

Your email address will not be published.