Take a fresh look at your lifestyle.

Ìpínlẹ̀ Kano Ń Ṣe ìdanilẹ́kọ̀ọ́  Bí Wọ́n Ṣe Lè Fi Orúkọ Sílẹ̀ Nípa Dígítà.

47

Ìgbìmọ̀ Àpapọ̀ Orílẹ̀-èdè Nàìjíríà (NPC), pẹ̀lú àjọpọ̀ pẹ̀lú Ẹgbẹ́ Àwọn Ìjọba Ìbílẹ̀ ti Orílẹ̀-èdè Nàìjíríà (ALGON) àti Ìgbìmọ̀ Ìṣàkóso Ìdánimọ̀ ti Orílẹ̀-èdè Nàìjíríà (NIMC), ṣe ìdánilẹ́kọ̀ọ́ ìmòye ọlọ́jọ́ méjì lórí ìforúkọsílẹ̀ nipa dígítà ní Ìpínlẹ̀ Kano, pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ láti ọ̀dọ̀ Ìjọ́ba Netherlands nípasẹ̀ UNICEF.

Ìdánilẹ́kọ̀ọ́ náà kó àwọn ènìyàn tí ó ń ṣe ìforúkọsílẹ̀ àti àwọn olùforúkọsílẹ̀ ìjọba agbègbè NPC áti gbogbo àwọn agbègbè ìjọba ìbílẹ̀ merinlelogoji ti ìpínlẹ̀ náà jọ.

Nígbà tí ó ń sọ̀rọ̀ níbi ìṣẹ̀lẹ̀ náà, Olùdarí Ìpínlẹ̀ NPC, Balarabe Kabir, sọ wí pé ètò náà jẹ́ láti mú kí agbára àwọn olùkọ́ni lágbára, tí wọn yóò sì fi  ni ìmọ̀ fún àwọn ènìyàn tí wọ́n ń ṣe ìtọ́jú àwọn ènìyàn  jákèjádò awọn ẹka ní Ìpínlẹ̀ Kano.

Ó ṣàlàyé wí pé ìdánilẹ́kọ̀ọ́ náà dojúkọ mímú kí lílo ohun èlò ìforúkọsílẹ̀ pàtàkì, ìpìlẹ̀ oní-nọ́ńbà fún ìforúkọsílẹ̀ ìbí oní-nọ́ńbà, tí a ń ṣe láti rí i dájú wí pé gbogbo ọmọ ni forúkọ sílẹ̀ dáadáa tí ó sì ní ìdánimọ̀ òfin.

Ìgbésẹ̀ yìí jẹ́ ara àwọn ìsapá tí ń lọ lọ́wọ́ láti mú kí ètò ìforúkọsílẹ̀ Orílẹ̀-èdè ní Nàìjíríà túbọ̀ gbòòrò sí i, kí a sì rí i dájú wí pé gbogbo ọmọ ni a ti dá mọ̀ láti ìgbà tí wọ́n bá ti bí wọn.

Comments are closed.

button