Guinea-Bissau ní àádọ́ta ọdún: Ààrẹ Tinubu darapọ̀ láti ṣàjọyọ̀ ayẹyẹ ọdún
Eyitayọ Fauziat Oyetunji
Ààrẹ Nàìjíríà Bọla Ahmed Tinubu ti gúnlẹ̀ sí Guinea-Bissau láti kópa nínú ayẹyẹ àyájọ́ àádọ́ta ọdún òmìnira àti ayẹyẹ àyájọ ológun.
Gẹgẹ bi alaye lati ọdọ agbenusọ aarẹ, Ajuri Ngelale, adari Naijiria yoo darapọ mọ awọn adari orilẹ-ede ati adari ijọba ni Bissu fun ayẹyẹ naa, ni ọjọ kẹrindin-logun, osu kọkanla 2023, leyi ti aarẹ Umaro Sissoco Embalo yoo gbalejo rẹ.
Guinea-Bissau sami ayẹyẹ ominira àádọ́ta ọdún, ni ọjọ kẹrinle-logun, oṣu kẹsan an 2023, ṣugbọn ijọba yi gbogbo ayeyẹ naa pada si ọjọ kẹrindin-logun. Oṣu kọkanla, 2023.
Aarẹ Tinubu yoo pada si Naijiria ni Ọjọbọ.
Leave a Reply