Ẹgbẹ́ Àwọn Oníròyìn VON Ké Gbàjarè Síta Bí Wọ́n Ṣe Pàdánù Ọ̀kan Lára Àwọn Akọ̀ròyìn Wọn, Hamisu Danjigba, Wọn Sì Bèrè Fun Ìwáàdí To Gbópọn.
George Ọláyínká Akíntọ́lá.
Pẹ̀lú Ibanujẹ Ọkàn ni Ẹgbẹ́ Àwọn Oníròyìn VON gba iroyin Ibanujẹ ikú Hamisu Danjigba, Akoroyin fún Ilé Akede Nàíjíríà (VON) ní Ìpínlẹ̀ Zamfara, iṣẹlẹ ibanujẹ yii to ṣele láti ọwọ́ àwọn ajínigbé.
Ikú rẹẹ̀ jẹ nkan Ibanujẹ tó tún ran wa létí irú ewu nla ti àwọn ọmọ Nàíjíríà wa ninu rẹ yìí nitori eto ààbò tó mẹ́ hẹ
A fẹ ki gbogbo iṣẹlẹ ibi yii dopin ni orílẹ̀-èdè wa, asi fi asiko yii bá àwọn mọ̀lẹ́bí olóògbé kẹdun, Ọlọrun yoo tẹ si afẹfẹ ire, iku rẹ o ni jẹ àkúfà
A ké pe àwọn Ologun, awọn adari waa, lati ṣe awari awọn to ṣe iku paá ki wọn si jìyà ẹṣẹ wọn.
Agbàálàdúrà lati maa ṣe agbako iru iṣẹlẹ yii mọ ninu Idile VON
Lákòtáán, Ki Ọlọrun ba wa tẹ HAMISU DANJIGBA safẹfẹ ire
TAWO GODWIN
AKỌ̀WÉ ẸGBẸ́
Leave a Reply