Ààrẹ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà, Bola Ahmed Tinubu, ṣé àpèjúwe Òṣìṣẹ́ ìjọba gẹ́gẹ́ bí ẹ̀rọ́ ìṣètò àti ìmúṣẹ ṣé àwọn ìlànà àti ètò ìjọba fún ìdàgbàsókè ètò ọrọ̀ ajé lápapọ̀ orílẹ̀-èdè náà.
Ààrẹ Tinubu sọ ọrọ̀ yìí níbí ọsẹ ayẹyẹ àwọn Òṣìṣẹ́ ìjọba ní Olú-ìlú Abùjá, Nàìjíríà.
Àkọwé Ìjọba tí Orílẹ̀-èdè Nàìjíríà, George Akume tó ń ṣoju Ààrẹ fí kún pé, Ààrẹ ní ìgbàgbọ́ nínú àwọn òṣìṣẹ́ wọnyí fún ìtèsíwájú àtí àgbéga.
Ààrẹ Tinubu gbóríyìn fún ọ̀gá àgbà òṣìṣẹ́ ìjọba àpapọ̀, Folashade Yemi-Esan fún ìríran rẹ̀ nípa ètò iṣẹ́ ìjọba túntún àti ìpinnu rẹ̀ láti ṣé bẹ́ẹ̀.
Leave a Reply