Ààrẹ Bọla Tinibu ti pinnu láti ṣàtúnyẹ̀wò lórí ìfọ̀rọ̀jomi toro ọ̀rọ̀ pẹ̀lú Chad láti kojú jàgídíjàgan àti adigunjalè ní Ẹkùn Lake Chad, tí ó sì ń fi ìdí ìpinnu Nàìjíríà múlẹ̀ láti ṣèmúdúró àjọṣepọ̀ ààbò láàrin àwọn méjèèjì.
O ṣe ipinnu yii ni Ọjọbọ, ni ile ijọba, ni Abuja, nigba ti o gbalejo Aarẹ Chad Muhamat Idriss Deby Itno, fun ifọrọjomi toro ọrọ to ṣe pataki lori aabo Ẹkun, idakọja aala to leto, ati idahun to tọ si awọn idunkẹkẹ ti n waye ni ẹka-Ẹkun naa.
O ṣe apejuwe abẹwo naa bii eyi to waye lasiko, Adari Naijiria ṣalaye pe ifọrọjomi toro ọrọ pẹlu Aarẹ Deby waye latari ipeninija aabo ti n koju Ẹkun naa, ti o si pe akiyesi pe Chad jẹ orilẹ-ede keji pataki ninu ajọṣepọ iṣe ologun ajọṣe ti o da ọpọlọpọ orilẹ-ede pọ (MNJTF).
Aarẹ Tinibu wa fikun un pe, orilẹ-ede mejeeji ti fẹnuko lati tẹramọ ajọṣepọ akitiyan lati koju jagidijagan, amukuroo idunkẹkẹ ipa, ati ikapa aabo ati ominira orilẹ-ede wọn.
O tun wa fidii ajọṣepọ ọlọjọ pipẹ to wa laarin orilẹ-ede mejeeji mulẹ, wipe awọn igbesẹ to n lọ lọwọ yoo da lori ipilẹ ti awọn adari to ṣaaju ti filelẹ lati ṣatunṣe lori iduruṣinṣin, ilọsiwaju, ọrọ-aje ati idagbasoke Ẹkun.