Àwọn ọmọ ẹgbẹ́ Agbábọ́ọ́lù Super Eagles ti bá Ààrẹ Bọla Tinubu lálejò ní ilé ìgbìmọ̀, ní ilé orílẹ̀-èdè, ní Abuja.
O n gbalejo wọn lẹyin ikopa wọn ninu ipele ikẹyin ninu idije ife awọn orilẹ ede Adulawọ (AFCON) 2024, ti o waye ni Côte d’Ivoire
Gbogbo awọn ọmọ ẹgbẹ naa ati oṣiṣẹ lo wa nijoko nibẹ afi Alex Iwobi ti o koju cyber-attacks nigba ti Cote D’Ivoire ja Naijiria danu ni ipele ikẹyin ninu idije ife awọn orilẹ-ede Adulawọ ti o ṣẹṣẹ pari yii.
A o ranti pe aarẹ Tinubu ti sọ ninu alaye kan ti o fi sita nipasẹ oludamọran pataki rẹ lori eto ibaraẹnisọrọ ati ipolongo, Ajuri Ngelale, ti o gboriyin fun ẹgbẹ naa, ati gbogbo awọn oluṣakoso ẹgbẹ naa fun iṣẹ ti wọn ṣe ninu ifigagbaga naa.
Aarẹ tun wa rọ awọn ọmọ Naijiria lati jẹ oniwuri, ti o si ṣalaye pe a gbiyanju fun Adulawọ, ti a si dara lagbaye, a fi agbara, ati ifọkansi han lori papa iṣere.