Take a fresh look at your lifestyle.

Ẹgbẹ́ Ọ̀dọ́ Niger Delta Rawọ́ Ẹ̀bẹ̀ Fún Àtìlẹyìn Láti Gbógunti Àrùn Ọpọlọ

80

Àjọ NDYC, ní Ọjọ́rún ti bèèrè fún àtìlẹyìn ìjọba àti àwọn ti ọ̀rọ̀ kàn láti gbógunti ìtànkálẹ̀ àrùn ọpọlọ ní àgbègbè náà

 

Ọ̀gbẹ́ni Jator Abido, tí ó jẹ́ alákòso àpapọ̀ fún àjọ NDYC ni ó pe ìpè náà níbi eré ìtagbangba tí ó wáyé ní ilé ìwé gíga Yunifásitì ti ìlú Port Harcourt, èyí tí ó ń pèpè fún àmójútó àti ìdènà fún àrùn ọpọlọ

 

Abido sàlàyé pé ètò ìdánilẹ́kọ̀ọ́ náà wáyé pẹ̀lú ìfọwọ́sowọ́pọ̀ láàrin Yunufásitì ti Port Harcourt, Àjọ NDDC, Àjọ Cradle ati NDYC. Ó sàpèjúwe ìgbésẹ̀ náà gẹ́gẹ́ bí èyí tí ó wáyé ní àsìkò tí ó sì se pàtàkì, èyí tí yóò ta àwọn alẹ́nulọ́rọ̀ jí láti gbógunti àìsàn àrùn ọpọlọ ní àgbègbè náà

 

Comments are closed.

button