Take a fresh look at your lifestyle.

Àjọ NLC Pàrọwà Sí Ìjọba, Ìjọ Ẹlẹ́sìn Gbogbo Láti Mú Ìgbòòrò Bá Ètò Ìlera

149

Ààrẹ Ẹgbẹ́ Òsìṣẹ́, Ọ̀gbẹ́ni Joe Ajero ti pàrọwà sí ìjọba àti àwọn ẹlẹ́sìn gbogbo láti gbé ìgbésẹ̀ èyí tí yóò mú ìdàgbàsókè bá ètò ìlera ní Orílẹ̀-èdè Nàìjíríà

 

Ajero sọ ọ̀rọ̀ náà nígbà tí ó ń sí ilé ìwòsàn èyí tí ìjọ ẹlẹ́sìn kan se àgbékalẹ̀ rẹ̀ ní àgbègbè Piwoyi, Ìlú Abuja

 

Ó gbósùbà fún alàgbà Ìjọ náà, Ọ̀jọ̀gbọ́n Emmanuel Musa fun àseyọrí ńlá tí ó wáyé láti ọwọ́ ìjọ Ọlọ́run náà, èyí tí ó wà fún àmúlò àti ìtọ́jú ọmọnìyàn. Ó wá rọ ìjọ ẹlẹ́sìn gbogbo láti kọ́se irúfẹ́ ìwà rere bẹ́ẹ̀ fún ìgbáyégbádùn ọmọnìyàn lápapọ̀

 

Comments are closed.

button