Toyin Abraham Mú Orílé Orílẹ̀-èdè United Kingdom Láti Sí Sinimá Tuntun Tí Àkọlé Rẹ̀ Jẹ́ “Malaika”.
Gbajú-gbajà eléré orí ìtàgé ọmọ Orílẹ̀-èdè Nàìjíríà, Toyin Abraham ti kéde fún gbogbo àgbáyé pé sinimá tuntun Òun yóò jáde ní Orílẹ̀-èdè United Kingdom ní ọjọ́ Ẹtì, ọjọ́ karùn-ún osù kíní ọdún 2024.
Toyin fi ọ̀rọ̀ náà léde lórí ẹ̀rọ ayélujára rẹ̀ ní ọjọ́ kejì osù kíní ọdún 2024. Ìrètí wà pé àjọ sinimá ilẹ̀ òkèèrè ni yóò rí sí pínpín káàkiri sinimá náà tí ìkéde yóò sì wáyé lórí àyè tí yóò ti bẹ̀rẹ̀ ní àìpẹ́ jọjọ
Ìgbésẹ̀ náà jẹ́ irúfẹ́ èyí tí Funkẹ Akindele se níbi sinimá rẹ̀ tí àkọlé rẹ̀ jẹ́ “Judah” ní Orílẹ̀-èdè United Kingdom ninu osu kejila ọdun 2023.