Ààrẹ Bọla Tinubu ti buwọ́lu yíyan Dókítà Ọlayẹmi Cardoso bíi Gómìnà ilé ìfowópamọ́ àpapọ̀ Nàìjíríà (CBN), fún sáà ọdún márùn ún fún ìbẹ̀rẹ̀, kí ilé ìgbìmọ̀ Nàìjíríà tó fìdí yíyàn rẹ̀ múlẹ̀.
Oludamọran pataki fun aarẹ lori ibaraẹnisọrọ ati ipolongo, Ajuri Ngelale lo fi idi yiyan yii mulẹ ninu alaye rẹ kan ti o si buwọlu.
Lafikun, aarẹTinubu tun buwọlu yiyan awọn igbakeji Gomina ile ifowopamọ apapọ ti Naijiria tuntun; Iyaafin Emem Usoro, Ọgbẹni Muhammad Dattijo, Ọgbẹni Philip Ikeazor, ati Dokita Bala Bello.
Awọn igbakeji gomina mẹrin tuntun ti o buwọlu yii yoo ṣiṣẹ fun saa ọdun marun fun ibẹrẹ, di igba ti ile igbimọ Naijiria yoo fi fidi yiyan wọn mulẹ.
Leave a Reply