Ìbúra fún àwọn Mínísítà márùndínládọ̀ọ́ta ti yóò bá Ààrẹ Tinubu ṣiṣẹ́ wáyé lóni ni ilé ìgbàlejọ̀ ìjọba àpapọ̀ ni ìlú Abuja.
Ààrẹ Tinubu, igbákejì Ààrẹ Shettima, Adarí ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin Goodwill Akpabio àti adari ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin keji Tajudeen Abbas ati awọn Gómìnà ìpínlẹ̀ ló péjú sí ìbi ibura náà.
![]()
Lẹ́yìn ọ̀sẹ̀ kán tí Ààrẹ Tinubu Yan àwọn Mínísítà náà ni ìbúra yìí wáyé
Ìbúra yìí ni wón se ni ìpele márùn-ùn ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀
Ìpele akọ́kọ́ ni wọn ṣe fún adájọ́ àgbà àti mínísítà fún ìdájọ́, Lateef Fagbemi, mínísítà fún ìpínlẹ̀ Nkiri Onyejiocha, Mínísítà fún ẹ̀kọ́ Tahir Mamman, Mínísítà fún ọ̀rọ̀ epo ìpínlẹ̀ Ekerikpe Ekoo ati Mínísítà fún àwọn Obìnrin Uju Ohaneywe.
Àwọn ipele tokun náà sì tèlé ní ké tí wọ́n ṣetán pẹ̀lú àwọn tó kún.
Leave a Reply