Alága ilé ìgbìmọ̀ aṣòfin lórí ọ̀rọ̀ àrùn kògbọ́ògùn, ikọ́ ife àti àìsàn ibà, Amobi Ogah ti rọ ìjọba Orílẹ̀-èdè Nàìjíríà láti kéde àìsàn ìbà gẹ́gẹ́ bí èyí tí o léwu julọ ti ó sì n ṣe iku pá ènìyàn.
Ogah ti o sójú Isuiwuato/Umunneochi láti ìpínlẹ̀ Abia, lo sọ èyí ni ìlú Abuja, ó ní bí a bá wo bi arun iba se ń kọlu Àwọn ènìyàn ó jẹ́ èyí tí o léwu púpọ̀ tí o sí n pa àwọn ènìyàn ní kíákíá.
Ó ní àwọn ìjọba nílò iṣé nlá lori àìsàn náà láti lè rí wí pé wọn Dẹkun rẹ là wú jọ
Ó ní kí ìjọba àpapọ̀ àti àwọn tọ́rọ̀ kan ri wí pé wọ́n ṣe atilẹyin fún àwọn òṣìṣẹ́ ìlera láti rí wí pé ọ̀rọ̀ àìsàn ibà di ohun ìgbàgbé ni Orílẹ̀-èdè Nàìjíríà
Ayẹyẹ ọjọ́ Àìsàn Ibà lágbayé wa n wáyé ni ogunjọ́ ninu osù kẹjọ, Àkọlé: tí ọdún yìí ni Bí bá àìsàn to n ṣe ikú pani já.
Ọ̀rọ̀ yìí wáyé láti lè jẹ kí àwọn ènìyàn mọ ìjàmbá ti ó wa nínú àìsàn ìbà àti láti Dẹkun rẹ ní gbogbo ọnà.
Leave a Reply