Take a fresh look at your lifestyle.

Àwọn ECOWAS Pàdé Ààrẹ Tinubu, Wọ́n Sí Ràn Aṣojú Lọ́ Sí Orílẹ̀-èdè Niger Republic

Ọlálékan Ọ̀rẹ́núgà

0 379

Aláṣẹ tí àwọn olórí orílẹ̀-èdè àti ìjọba tí ẹgbẹ́ Ìwọ̀-oòrùn Áfíríkà (ECOWAS) tí rán Ààrẹ Orílẹ̀-èdè Benin, Patrice Talon lọ́ sí Niamey, Republic of Niger, látí lọ́ dẹkùn ìdààmú òṣèlú ní orílẹ̀-èdè náà.

Alága tí ECOWAS àti Ààrẹ Nàìjíríà, Bola Tinubu, sọ èyí fún àwọn oníròyìn Ilé-iṣẹ́ Ìjọba àpapọ̀, lẹyìn tí òún Ààrẹ Talon ṣé ìpàdé lẹyìn ilẹkùn ní Abuja.

Ó ní: “Ó ń lọ síbẹ̀ nísinsìnyí; o tí wà ní ọnà rẹ̀ bayii sí Niger Republic.”

Ìpàdé láàrín àwọn Olùdarí méjèèjì jẹ́ tí pajawiri látí lè wá ọnà àbáyọ́ sí rògbòdìyàn tó ń lọ́ lọ́wọ́ ní Niger Republic.

Bákan náà, Ààrẹ orílẹ̀-èdè Benin, Patrice Talon tó ń ṣèbẹ̀wò sí orílẹ̀-èdè Niger Republic tó wà ní àdúgbò rẹ̀ jẹ́ oun tó le gan-an, ó sì yẹ kí wọ́n gbé ìgbésẹ̀ kíákíá láti ṣé àtúnṣe sí.

Talon sọ ìrètí rẹ̀ pé òún gbàgbọ́ pé ìgbésẹ ECOWAS náà yóò yọrí sí réré.

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *

button