Gbajúgbajà olórin ọmọ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà Davido ti gúnlẹ̀ sí orílẹ̀ èdè Qatar, léyìí tí ó sì yọjú sí ibi àsekágbá ayẹyẹ eré ìdárayá ife ẹ̀yẹ àgbáyé ( FIFA 2022 World Cup).
Ó yẹ kí ó ti se eré náà ní ìbẹ̀rẹ̀ eré ìdíje bọ́ọ̀lù aláfẹsẹ̀gbá náà sùgbọ́n kò ní ànfààní láti se bẹ́ẹ̀ látàrí ìsẹ̀lẹ̀ láabi tí ó sẹlẹ̀ síi.
Eré ṣíṣe rẹ níbi ayẹyẹ àsekágbá ife ẹ̀yẹ àgbáyé ní ọjọ́ Àìkú (Sunday) ọjọ́ kejìdínlógún osù kejìlá (December, 18) jẹ́ àkọ́kọ́ lẹ́yìn ìgbà tí o pàdánù ọmọ rẹ̀.
Leave a Reply