Take a fresh look at your lifestyle.

DOWEN COLLEGE: A ò ní dá àwọn tó pa Oromoni sí, a ó fi ọwọ́ òfin mú wọn-Buhari

0 375

Aarẹ Muhammadu Buhari  ti ni awọn to pa  Sylvester Oromoni, to jẹ ọmọ ile-ẹkọ  Dowen to wa ni  Lekki ní ipinlẹ Eko kò ní fara ire lọ.

Ọmọ ọdun mejila ọhun, ni a gbọ pe awọn akẹgbẹ seku paa  nile ẹkọ to wa , latari bi wọn se se ọmọ ọhun ni ijamba, ni eyi ti o gbẹmi ọmọ naa.

Aarẹ  Buhari fi aidunnu rẹ han bi wọn se pa ọmọkunrin ọhun wa nile ẹkọ to wa , wa ni ; “To ba se pe loootọ ni ọmọkunrin naa ku, nipase, bi wọn se fẹ mu wọ inú ẹgbẹ́ okunkun tabi bi wọn se fi ìyà aitọ jẹẹ, iyẹn a gbọdọ wa nnkan se si isẹlẹ buruku ọhun.

“Mo ba awọn ẹbi Oromoni, ijọba ipinlẹ Eko ati orilẹ ede Naijiria kẹdun lori isẹlẹ naa, mo si fi n  da wọn loju pe, ao se ikwadii isẹlẹ buruku, ti ao si fi gbogbo awọn to lọwọ ninu isẹlẹ naa jofin. ,”

Aarẹ Buhari wa rọ awọn gbofinro ati ile-isẹ ọlọpaa lati se iwadii finni-finni  nipa isẹlẹ ọhun.Ki wọn si fi ọwọ ofin mu gbogbo awọn to lọwọ ninu isẹlẹ naa, laifi da ẹnikankan si.

 

 

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *

button