Ìjọba Nàìjíríà ti kéde ètò láti dá ilé-ẹ̀kọ́ ìṣègùn àti sáyẹ́ǹsì ìlera (Armed Forces College Of Medicine and Health Sciences AFCOM&HS) sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí apá kan nínú àwọn ìsapá láti mú kí ìtọ́jú ìlera lágbára síi láàrín àwọn ológun àti láti mú kí agbára ìdánilẹ́kọ̀ọ́ ìṣègùn Nàìjíríà gbòòrò síi.
Èyí ni a sọ nínú ìkéde kan tí Olùdarí Ìròyìn àti Àjọṣepọ̀ Gbogbogbòò ní Ilé-iṣẹ́ Ẹ̀kọ́ ti Àpapọ̀, Folasade Boriowo, fi sílẹ̀.
Ní aṣojú Mínísítà fún Ẹ̀kọ́, Dókítà Tunji Alausa, Boriowo ṣe ìkéde náà nígbà ìpàdé gíga pẹ̀lú Mínísítà fún Ààbò, Ọgágun Christopher Musa tó ti fẹ̀yìntì, àti àwọn alẹnu-lọrọ pàtàkì. Àwọn mìíràn tí wọ́n tún wà níbi ìpàdé náà ni Mínísítà fún Ẹ̀kọ́, Ọ̀jọ̀gbọ́n Suwaiba Ahmad, àti Mínísítà fún Ààbò, Dókítà Bello Matawalle.
Gẹ́gẹ́ bí Alausa ti sọ, ilé-ẹ̀kọ́ náà bá ètò àtúnṣe gbogbogbòò ti Ìjọba Àpapọ̀ mu, pàápàá jùlọ àwọn ètò tí a gbé kalẹ̀ láti mú kí ẹ̀kọ́ Sáyẹ́ǹsì, Ìmọ̀-ẹ̀rọ, Ìmọ̀-ìṣirò àti Ìmọ̀-ẹ̀rọ Ìṣègùn lágbára síi.
Comments are closed.