Ẹkún Gbọn Ikọ̀ Super Eagles Nàìjíríà Nígbà Tí Wọn Kùnà Láti Pegedé Fún Ìdíje Ife Àgbáyé Qatar 2022.
Ikọ̀ agbábọ́ọ̀lù Black Stars Ghana ti pegedé fún ìdíje ife àgbáyé Qatar 2022 látàrí bí wọ́n sẹ já ikọ̀ Super Eagles Nàìjíríà nínú ìfẹsẹ̀wọnsẹ̀ to waye ọjọ́ Ìsẹ́gun, ni papa isere MKO Abila to wa ní ìlú Abuja.
Àmi ayọ̀ 1-1 ni wọ́n gbá nínú ìfẹsẹ̀wọnsẹ̀ náà. Thomas Partey ló kọ́kọ́ jẹ góòlù fún ikọ̀ Black Stars nígbàtí William Troost-Ekong gbá pẹnáritì fún ikọ̀ Nàìjíríà.
Ikọ̀ Super Eagles là kàkà láti ri wípé wọn jáwé olúborí sùgbọ́n, omi pọ̀ ju ọkà wọn lọ.
Tolulope Henry
Leave a Reply