Take a fresh look at your lifestyle.

NAWOJ Ìpínlẹ̀ Ogun Kẹ́dùn Ikú Bukola Agbakaizu

Lekan Orenuga

144

Ẹgbẹ́ Akọ̀ròyìn Obínrin lórílẹ̀-èdè Nàìjíríà (NAWOJ) ẹká tí Ìpínlẹ̀ Ogun tí fí ìbànújẹ ọkàn wọ́n hàn lórí ikú ọkán lára àwọn ọmọ ẹgbẹ́ wọ́n, Iyaafin Bukola Agbakaizu.

‎ Ìyáfín  Agbakaizu, ẹni ọdún méjìlèlàádọta, tún jẹ́ ọkan nínú àwọn ọmọ ẹgbẹ́ oníròyìn (Nigeria Union of Journalists, NUJ), tí Ìpínlẹ̀ Ogun àti òṣìṣẹ́ ilé-iṣẹ́ tẹlifísàn ìpínlẹ̀ Ogun (OGTV). Wọ́n sọ pé o ṣubu lọ́jọ́ Àjé tó kọjá yí lásìkò tó ń múra fún iṣẹ́ tí ọsán, tí wọ́n sí gbìyànjú sáré gbé lọ sí ilé-ìwòsàn tí ìjọba àpapọ̀ tó wà ní Idi-Aba, Abeokuta, níbí tí wọ́n tí sọ pé o tí kú.

‎ Nínú àlàyé ìtùnú tí Alága NAWOJ tí Ogun, Sekinat Salam fọwọ́sí, ikú Ìyáfín Agbakaizu jẹ́ kayefi sí gbogbo àwọn ọmọ ẹgbẹ́. O sí gbá làdúrà pé kí Oluwa tẹ́ sí afẹ́fẹ́ iré.

Comments are closed.

button