Ẹgbẹ́ Òsèlú APC ti bẹ̀rẹ̀ ìwọlé ní ojúlé sí ojúlé láti ta àwọn alátìlẹyìn, ọmọ ẹgbẹ́ náà jí jákè-jádò ìjọba ìbílẹ̀ mẹ́tàlá tí ó wà ní Ìpínlẹ̀ Ebonyi
Alága ẹgbẹ́ náà ti Ìpínlẹ̀ Ebonyi, Stanley Okoroemegha ni ó síṣọ lójú ọ̀rọ̀ náà nígbà tí ó ń bá àwọn akọ̀ròyìn sọ̀rọ̀ ní ọ́ọ́fìsì ẹgbẹ́ náà, èyí tí ó wà ní Abakaliki, olú ìlú Ìpínlẹ̀ náà
Emegha salaye pé ìtanijí náà se pàtàkì nítorí pé lẹ́yìn ìpolongo ìdìbò tí ó kọjá, ẹgbẹ́ náà kò ì tí ì se àbẹ̀wò sí àwọn alátìlẹyìn rẹ̀ ní ibùgbé wọn
Ó wá lo ànfààní náà láti se àfọ̀mọ̀ awuyewuye tí ó ń lọ wípé wàhálà wà láàrin gómìnà Ìpínlẹ̀ Ebonyi, Francis Nwifuru ati Mínísítà Fún Àkànṣe Iṣẹ́, David Umahi