Ààrẹ Bọla Tinubu ti kí Dókítà Chidia Maduekwe, Alákòóso Adarí ìgbìmọ̀ tí ń ṣàmójútó Fíìmù ní Nàìjíríà (NFC), kú oríire bí ó ṣe ń ṣàjọyọ̀ àádọ́rin ọdún ọjọ́ ìbí rẹ̀.
Ninu ọrọ re kan ti agbenusọ aarẹ, Ajuri Ngelale buwọlu, aarẹ Tinubu ṣapejuwe Asofin tẹlẹ ri, ti o di ipo kan mu ni ile igbimọ Aṣoju lasiko iṣejọba lorilẹ-ede lẹlẹẹkẹta, gẹgẹ bi oṣiṣẹ ijọba to niyi ati ọga alafọkansin ikọ fiimu Naijiria.
“Mo ṣajọyọ pẹlu Dokita Chidia Maduekwe ti o pe aadọrin ọdun ti o daye. O jẹ ọkunrin to ṣe aṣeyege loriṣiris,i ti o si fi ọdun marunle-lọgbọn aye rẹ sin orilẹ -ede ni oriṣiriṣi ọna,”.
Aarẹ wa gbadura si ọlọrun ki o fun ni ẹmi gigun, alaafia, ati ọpọlọpọ ọgbọn lati tẹsiwaju lori sisin orilẹ ede.
Leave a Reply