Ẹgbẹ́ òṣèlú All Progressives Congress (APC) ti kéde pé wọ́n ń mú kí agbára ìjọba wọn lágbára sí i ní gbogbo orílẹ̀-èdè Nàìjíríà lábẹ́ ìdarí Ààrẹ Bola Tinubu, ó sì tọ́ka sí àwọn àṣeyọrí ìgbìmọ̀ aṣòfin àti ìṣàkóso ìjọba ni ìpínlẹ̀ Ọgbọ̀n gẹ́gẹ́ bí ẹ̀rí pé wọ́n ń gba ìtẹ́wọ́gbà òṣèlú.
Akọ̀wé apapọ ti ẹgbẹ oṣelu APC, Sẹ́nétọ̀ Ajibola Bashiru, ẹni tí ó bá àwọn akọ̀ròyìn Ilé Ìgbìmọ̀ sọ̀rọ̀ lẹ́yìn ìpàdé rẹ̀ pẹ̀lú Ààrẹ ní Ilé Ìgbìmọ̀, Abuja, kéde pé ète Ààrẹ Tinubu ni láti kọ́ ẹgbẹ́ òṣèlú kan olotitọ tí ó ní èrò gbogbogbòò ní Nàìjíríà.
Ó sọ pé àwọn ìdàgbàsókè nínú ẹgbẹ́ òṣèlú APC ṣe àfihàn ẹgbẹ́ òṣèlú kan tí ó ń lágbára sí i tí ó sì ń sopọ̀ mọ́ ara wọn ní gbogbo orílẹ̀-èdè yii.
Tèmítọ́pẹ́ Òbísẹ̀san