Mínísítà fun Agbegbe Olu-ilu Apapo Orílẹ̀-èdè Nàìjíríà Abuja Nyesom Wike, ti yin Ààrẹ Bola Tinubu fun fífọwọ́ sí Òfin Ìdìbò ti odun 2026 (Àtúnṣe) ní kíákíá.
Nínú ìròyìn kan tí Olùrànlọ́wọ́ pàtàkì rẹ̀ lórí Ìbánisọ̀rọ̀ gbogbogbòò àti Ìròyìn Àwùjọ, Lere Olayinka, gbé jáde ní ọjọ́rú, ni ọ̀rọ̀ tí jáde.
Minisita ṣàpèjúwe ìgbésẹ̀ Ààrẹ gẹ́gẹ́ bí ẹ̀rí síwájú síi ti ìdúróṣinṣin rẹ̀ láti mú kí ìlànà tiwantiwa lágbára síi àti láti mú kí ìgbẹ́kẹ̀lé àwọn ìdìbò pọ̀ sí i ní orílẹ̀-èdè náà.
Wike sọ wí pé gbígba Òfin Ìdìbò tí a ṣe àtúnṣe sí láti ọwọ́ Ààrẹ, lẹ́yìn náà ìfọwọ́sí kíákíá ti Ààrẹ, ti fòpin sí ohun tí ó pè ní ìfẹ̀hónúhàn tí kò pọndandan láti ọwọ́ àwọn ènìyàn tí wọ́n sọ wí pé wọ́n ń múra àwáwí sílẹ̀ fún ìjákulẹ̀ ìdìbò tí ó ń bọ̀.
Ó sọ wí pé, “Ìjọba tiwantiwa ti jẹ́ iṣẹ́ tí ń lọ lọ́wọ́ nígbà gbogbo, bí ó ti ń yí padà nígbà gbogbo,” ó fi kún un pé nípa ṣíṣe àtúnyẹ̀wò Òfin Ìdìbò nígbà gbogbo pẹ̀lú èrò láti mú kí ìlànà tiwantiwa lágbára síi, “ó dájú pé a ó máa tẹ̀síwájú láti mú un sunwọ̀n síi.”
Ààrẹ Bola Tinubu ti fọwọ́ sí Òfin Ìdìbò 2026 (Àtúnṣe) gẹ́gẹ́ bí òfin, ọjọ́ díẹ̀ lẹ́yìn tí Ìgbìmọ̀ Ìdìbò Orílẹ̀-èdè Olómìnira (INEC) ti tú àkójọ ìdìbò gbogbogbòò ọdún 2027 jáde, lẹ́yìn ọ̀pọ̀ ìjíròrò àti àríyànjiyàn lórí ìgbékalẹ̀ rẹ̀ láti ọwọ́ Ìgbìmọ̀ Àgbà.
Ayẹyẹ ìfọwọ́sowọ́pọ̀ náà wáyé ní Ilé Ìgbìmọ̀ Àgbà, Abuja, ní nǹkan bí agogo márùn-ún ìrọ̀lẹ́ ní ọjọ́rú, pẹ̀lú àwọn olórí ilé ìgbìmọ̀ Àgbà ti o wà níbẹ̀.