Ìgbìmọ̀ Ìṣàkóso Ìdánimọ̀ ti Orílẹ̀-èdè Nàìjíríà (NIMC), sọ wí pé ó ti múra tán láti bẹ̀rẹ̀ ìforúkọsílẹ̀ ní ìpele gbogbo orílẹ̀-èdè Nàìjíríà fún ìforúkọsílẹ̀ Nọ́mbà Ìdánimọ̀ (NIN) ní ìbámu pẹ̀lú àṣẹ Ààrẹ tí ó pàṣẹ fún Ìgbìmọ̀ Ìṣàkóso Ìdánimọ̀ ti Orílẹ̀-èdè Nàìjíríà láti mú ìforúkọsílẹ̀ NIN lọ sí àwọn agbègbè gbogbo ní Nàìjíríà orílẹ̀-èdè.
Nínú ìkéde kan láti ọwọ́ Ìgbìmọ̀ náà, ajo NIMC kéde wí pé ìforúkọsílẹ̀ fún ìfiránṣẹ́ Nọ́mbà Ìdánimọ̀ ti Orílẹ̀-èdè Nàìjíríà (NIN) ní àwọn agbègbè gbogbo orílẹ̀-èdè yóò bẹ̀rẹ̀ ní ọjọ́ Ajé, ọjọ́ kẹrìndínlógún oṣù kejì, ọdún 2026.
Gẹ́gẹ́ bí ìkéde náà ti sọ, a ṣe ètò ìforúkọsílẹ̀ ní gbogbo orílẹ̀-èdè Nàìjíríà náà láti rí i dájú pé gbogbo ọmọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà àti olùgbé lábẹ́ òfin, títí kan àwọn ọmọdé àti àgbàlagbà sínú ibi ìpamọ́ ìdánimọ̀ ti Orílẹ̀-èdè Nàìjíríà ni a ṣe àkíyèsí pé ìforúkọsílẹ̀ náà yóò wáyé lọ́fẹ̀ẹ́, ní ìtẹ̀síwájú ètò ìrètí tuntun ti Ààrẹ Bola Ahmed Tinubu tí ó ní èrò láti gbé ìṣàkóso gbogbogbòò, ìdàgbàsókè orílẹ̀-èdè, àti àǹfààní sí àwọn iṣẹ́ ìdánimọ̀ lárugẹ.
Ó tún sọ wí pé ètò ìforúkọsílẹ̀ ní ìpele ìpele dúró fún ìgbésẹ̀ pàtàkì sí jíjinlẹ̀ sí ìfàmọ́ra ìdánimọ̀, pípín àwọn iṣẹ́ sípò, àti mímú ìforúkọsílẹ̀ dé ìpele, Ó ṣe àkíyèsí wí pé ìṣètò ìforúkọsílẹ̀ ní ẹ̀ka ìtọ́jú àwọn òṣìṣẹ́ tí ó ní ìwé àṣẹ àti àwọn òṣìṣẹ́ NIMC ni a lè rí lórí ojú-òpó wẹ́ẹ̀bù (NIMC: www.nimc.gov.ng ) àti fún àwọn ìbéèrè síwájú síi, ìrànlọ́wọ́, tàbí ìpinnu ẹ̀sùn, a gba àwọn ènìyàn níyànjú láti pe laini owó tí a fi ń pe NIMC láìsanwó nípasẹ̀ nọmba yii 08000616462