Ìjọba Nàìjíríà ti fi àníyàn ńlá hàn lórí àwọn ọ̀ràn tó ń pọ̀ sí i nípa bí àwọn ọmọ-ìlú Nàìjíríà ṣe ń kópa nínú àwọn ìjà ológun olówó-ìlú láti orílẹ̀-èdè mìíràn, ó kìlọ̀ pé irú àwọn ìgbòkègbodò bẹ́ẹ̀ lè fa ewu ńlá sí ẹ̀mí àti pé wọ́n rú òfin orílẹ̀-èdè àti ti àgbáyé.
Èyí ni a sọ di mímọ̀ nínú ìkéde kan tí agbẹnusọ fún Ilé-iṣẹ́ ilẹ̀ Òkèèrè, Kimiebi Ebienfa, fi hàn pé àwọn ìwádìí àti ìròyìn ààbò láìpẹ́ yìí fi hàn pé ọ̀pọ̀ àwọn ọmọ-ìlú Nàìjíríà ni wọ́n gbà síṣẹ́ lábẹ́ ẹ̀tàn èké, títí bí ìlérí iṣẹ́ tó ń mówó wọlé, iṣẹ́ ààbò, àǹfààní ẹ̀kọ́, tàbí ìṣírí ìrìnàjò.
Ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn wọ̀nyí ni wọ́n sọ pé ẹ̀tàn àti ifipá muni tọwọ bọ ìwé àdéhùn iṣẹ́ ológun ní àwọn fí bá ará àwọn nínú ìṣòro náà.
Ní ọrọ kan, wọn fipá mú wọn láti fọwọ́ sí àwọn ìwé àdéhùn tí èdè àjèjì tí wọ́n fí kọ́ ìwé náà kò yé wọn láìsí ìtọ́sọ́nà òfin tó tọ́, pẹ̀lú ifipá gbà àwọn ìwé ìrìnàjò wọn nígbà tí wọ́n dé. Àwọn ìròyìn tún fi hàn pé àwọn alárinà tí wọ́n ń ṣe ìrànlọ́wọ́ fún ìrìnàjò lábẹ́ àwọn ẹ̀ka fíísà arìnrìn-àjò tàbí àwọn ẹ̀ka fíísà tí kì í ṣe ti ológun mìíràn.
Ijọba Naijiria kilọ fun awọn ara ilu ni gbangba pe ki wọn má ṣe gba eyikeyi ipese ti o ni ipa ninu awọn ija ogun ilẹ̀ Òkèèrè, o si tẹnumọ pe iru awọn iṣe bẹẹ n fi ẹmi sinu ewu ati pe o le tako awọn ofin ti n ṣakoso awọn iṣẹ aṣofin ati fifi orukọ silẹ lati okeere.
Comments are closed.