Agbẹjọ́rò Àgbà fún Jersey, Mark Temple KC, ti fọwọ́ sí ìwé àdéhùn ìmòye (MoU) pẹ̀lú Nàìjíríà láti mú kí owó tó ju $9.5 mílíọ̀nù tí wọ́n jí padà fún ìjọba Nàìjíríà fún ìrọ̀rùn, èyí tí yóò pèsè àwọn ohun èlò míràn fún àwọn iṣẹ́ ètò ìdàgbàsókè pàtàkì.
Èyí ni a sọ nínú ìkéde láti ọwọ́ Ìgbìmọ̀ Gíga ti Ilẹ̀ Gẹ̀ẹ́sì sí Nàìjíríà.
Gẹ́gẹ́ bí gbólóhùn náà ti sọ, àwọn owó tí wọ́n gbà padà yóò ṣètìlẹ́yìn fún àwọn iṣẹ́ ètò ìdàgbàsókè pàtàkì ní Nàìjíríà.
Agbẹjọ́rò Àgbà ti Àpapọ̀ àti Mínísítà fún Ìdájọ́ Nàìjíríà, Lateef Fagbemi nígbà tí ó ń gbà àdéhùn náà, ó sọ pé: “Ìgbàpadà àti dídá àwọn dúkìá tí wọ́n pàdánù padà, tẹnumọ́ bí àwọn ìsapá ìfọwọ́sowọ́pọ̀ Nàìjíríà pẹ̀lú àwọn alábàáṣiṣẹpọ̀ àgbáyé rẹ̀ ṣe ń rí i dájú pé kò sí ibi ààbò fún ọrọ̀ tàbí dúkìá tí wọ́n kó lọ sí àwọn agbègbè òkèèrè.”
Ó dúpẹ́ lọ́wọ́ Bailiwick ti Jersey O sí ṣé ìdánilójú fún lílo owó tí wọ́n dá padà náà dáadáa.
Èyí ṣàfihàn ìsapá Nàìjíríà láti tọ́pasẹ̀ owó tí wọ́n jí ko, gbà padà àti láti fi wọn ṣiṣẹ́ ìdàgbàsókè orílẹ̀-èdè.
Comments are closed.