Take a fresh look at your lifestyle.

Mínísítà Fún Ilé-iṣẹ́ Abẹ́lé Rọ NSCDC Láti Fí Ọgbọ́n Tó Dára Ṣiṣẹ́ Ààbò ‎

100

Mínísítà fún Ilé-iṣẹ́ Abẹ́lé, Dokita Olubunmi Tunji-Ojo, tí rọ Ilé-iṣẹ́ Ààbò àti Ààbò Aráàlú Nàìjíríà (NSCDC) láti mú ọgbọ́n àti òye pẹ̀lú òfin ló lórí ìṣẹ́ ààbò ìlú láti mú ètò ààbò orílẹ̀-èdè náà lágbára sí i.

‎Nigba tó ń sọrọ níbi ayẹyẹ ọṣọ kan, Mínísítà náà yín àwọn ìgbìyànjú NSCDC ní mímú ààbò orílẹ̀-èdè pọ̀ sí lórí ààbò àwọn ohun-iní àti àwọn amayedẹrun orílẹ̀-èdè pàtàkì, àti ẹmi.

‎O tún sọ ìwúlò láti ṣe ìlànà àwọn ọgbọ́n láti kojú àwọn irọkẹ̀kẹ ẹ̀rù ti n yọ jáde sí àlàáfíà àti ìdàgbàsókè orílẹ̀-èdè.

‎Rt. Major General Abdulmalik Jibrin (CDCFIB) ló sojú fún Mínísítà níbi ayẹyẹ náà.

‎ Alàkóso Gbogbogbò NSCDC, Ọ̀jọ̀gbọ́n Ahmed Abubakar Audi nínú ọrọ rẹ̀, pàṣẹ fún àwọn òṣìṣẹ́ lórí ìwúlò láti kọ àwọn ọmọ abẹ́ wọn pẹ̀lú ìmọràn, O kikọ fún wọn pé wọn láti gbà àwọn ojúṣe wọn gẹ́gẹ́ bí olórí túntún ní àwọn ẹka wọn.

Comments are closed.

button