Bí Super Eagles ṣe ń múra sílẹ̀ fún ifẹsẹwọnsẹ wọn nínú ìdíje bọ́ọ̀lù Adúláwọ̀ “African Cup of Nations” (AFCON) ní ìpele oníkọ̀ mẹ́rìndínlógún pẹ̀lú Mozambique ní ọjọ́ karùn-ún oṣù kìíní, ọdún 2026, àwọn òun márùn-ún wọ̀nyí ló ń ṣẹlẹ̀ sí ikọ náà ní àgọ́ wọn;
– Àwọn agbábọ́ọ̀lù malárùndínlọ́gbọ̀n ní wọn kopa nínú ìkọ́ni tí alẹ́ ọjọ́ Ẹtì
– Ryan Alebiosu wà ní ìpàgọ́ ẹgbẹ́ náà ṣùgbọ́n kò kópa latari ìlera rẹ̀.
– Ìpalára itan ti mú kí Cyriel Dessers kúrò nínú ìpàgọ́ ẹgbẹ́ náà. Ó ti padà sí ẹgbẹ́ agbábọ́ọ̀lù rẹ̀ báyìí.
– Tochukwu Nnadi náà kó kópa latari àárẹ̀ ránpẹ́ tí òtútù.

– Olùkọ́ni àgbà Eric Chelle ti sọ fún àwọn agbábọ́ọ̀lù náà láti fi àwọn àṣeyọrí ìpele akọ́kọ́ sẹyìn kí wọ́n sì dojúkọ ìpele tó kù níwájú.
Super Eagle tí Nàìjíríà ní yóò waako pẹ̀lú Mòsámbìk ni ọjọ́ Ajé, ọjọ́ kárún-ùn, oṣù kìíní, ọdún 2026.