Take a fresh look at your lifestyle.

Ìtọ́nisọ́nà Ṣé Pàtàkì Sí Ìgboyà Láti Darí Gẹ́gẹ́bí Aṣáájú Dáadáa – Mínísítà

82

Mínísítà fún Ìròyìn àti Ìtọ́sọ́nà Orílẹ̀-èdè Nàìjíríà, Mohammed Idris, ti tẹnu mọ́ ìmọ̀ràn àti ìtọ́sọ́nà gẹ́gẹ́ bí òun pàtàkì sí ìgboyà fún ẹnikẹ́ni láti darí bí aṣáájú réré.

 

‎ Mínísítà fún Ìròyìn sọ ọ̀rọ̀ yìí níbi ìpàdé kan tí àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀ àtijọ́ àti lọ́wọ́lọ́wọ́ láti ilé-iṣẹ́ ìròyìn rẹ̀ ní Kaduna ṣe ní ọlá rẹ̀.

 

‎Èyí ni a sọ nínú ìkéde kan tí Olùrànlọ́wọ́ Pàtàkì (Ìròyìn) fún Mínísítà Ìròyìn àti Ìtọ́sọ́nà Orílẹ̀-èdè náà, Rabiu Ibrahim fọwọ́ sí.

‎Nígbà tí ó ń ronú nípa ogún ọdún, Idris tẹnu mọ́ ìdàgbàsókè tó gbòòrò sí àwọn ilé-iṣẹ́ ìròyìn rẹ̀ àti àwọn ògbóǹtagí tí wọ́n tọ́ dàgbà nínú wọn.

‎Ó fi ìdùnnú rẹ̀ hàn nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ènìyàn tí wọ́n bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ wọn lábẹ́ ìtọ́sọ́nà rẹ̀ tí wọ́n sì ti dé ipò pàtàkì, tí wọ́n ń ṣe àfikún gidigidi sí ìdàgbàsókè orílẹ̀-èdè ní onírúurú ẹ̀ka.

 

‎O ṣé àfiwé èròngbà rẹ̀ ti ìṣàkóso Ààrẹ Bola Ahmed Tinubu, Idris ṣàlàyé bí ìmọ̀ràn ìtọ́nisọ́nà ṣe ń kọ́ni ní agbára, ọgbọn àti ìgbẹ́kẹ̀lé tó ń fún-ní ní ìgboyà láti darí gẹ́gẹ́ bí aṣáájú.

Comments are closed.

button