Ààrẹ Bola Tinubu kéde àtúnṣe tí Ìgbìmọ̀ Eré Ìdárayá tí Orílẹ̀-èdè Nàìjíríà (National Sports Commission NSC) tó tí wá fún ìgbà pípẹ́ láti dáàbòbo ìṣàkóso eré ìdárayá kúrò lọ́wọ́ àwọn ìdádúró ìjọba àti àwọn ìdíwọ́ mìíràn.
Ààrẹ ló sọ èyí nígbà tó kéde ìbẹ̀rẹ̀ eré ìdárayá tí Orílẹ̀-èdè ikejìlèlogún irú rẹ̀ ní àjọṣe àrà ọ̀tọ̀ tí wọ́n ń pè ní ‘Gateway Games Ogun 2024’ nílùú Abeokuta, Olú ìlú ìpínlẹ̀ Ogun.
Ààrẹ náà tí igbákejì rẹ̀ Kashim Shettima sójú ní Abeokuta, sọ pé ìpinnu ìṣàkóso rẹ̀ yóò ṣé àfihàn ìṣàkóso pàtàkì fún àwọn eré ìdárayá Orílẹ̀-èdè nítorí ipá pàtàkì tí ẹka náà ń ṣé ní orílẹ-èdè.
Comments are closed.