Take a fresh look at your lifestyle.

Aṣáájú Nàìjíríà Jẹ́jẹ̀ẹ́ Láti Sápá Òun Síi Lórí Ààbò Oúnjẹ ‎

Lekan Orenuga

226

Ààrẹ Nàìjíríà, Bola Ahmed Tinubu tí ṣé ìlérí láti túbọ̀ sápá òun sí lórí àṣeyọrí oúnjẹ, ìdókòwò àti ìdàgbàsókè jákèjádò orílẹ̀-èdè náà.

‎ O ṣé ìlérí náà ní Abuja, Olú-ìlú Orílẹ-èdè l’àkókò tí gbogbo àwọn ọmọ ‘All Progressive Congress APC’, fí ìgbàgbọ́ wọ́n hàn gẹ́gẹ́ bí adari réré.

‎ Ààrẹ Tinubu ṣàpèjúwe ìgbàgbọ́ àwọn ọmọ ẹgbẹ́ náà gẹ́gẹ́bí ìpèníjà láti ṣiṣẹ́ takun-takun síi àti látí mú ìdàgbàsókè bá ètò-ọrọ àjé orílẹ̀-èdè Nàìjíríà jú tilẹ̀ lọ́.

‎ Ìpàdé Ìgbìmọ̀ Àwọn Aláṣẹ tí ‘APC’ náà ló wáyé ní Ọjọ́rú. Níbí ìpàdé náà ní àwọn Olùdarí ẹgbẹ́ náà tún gbóríyìn fún ìṣàkóso Ààrẹ Tinubu fún yiyi ọrọ-àjé Orílẹ̀-èdè náà pàdà sí dáadáa.

Comments are closed.

button