Orílẹ̀-èdè Nàìjíríà Ta Kókó Ìbásepọ̀ Pẹ̀lú United States Lórí Ìdàgbàsókè Àjọ Ọmọ Ogun
Akọ̀wé Àgbà ní ẹka ìjọba àpapọ̀ fún ìdáàbò bò ìlú, Ibrahim Kana ti sọ pé ìjọba àpapọ̀ yóò tẹ̀síwájú nínú ìbásepọ̀ rẹ̀ pẹ̀lú Orílẹ̀-èdè United States lórí ìdàgbàsókè àjọ ọmọ ogun
Kana sọ ọ̀rọ̀ náà nígbà tí ó gba àlejò àwọn asojú United States ní ọ́ọ́fìsì àpapọ̀ ẹka ètò àbò ní ìlú Abuja
Ó sàlàyé pé Orílẹ̀-èdè Nàìjíríà ti kó ipa pàtàkì láti jẹ́kí àlàáfíà jọba ní àwọn Orílẹ̀-èdè adúláwọ̀ bíi Mali, Liberia, Equitorial, South Africa, Sierra Leone, Gambia, Guinea, Sudan Ati Chad