Ọkàn nínú àwọn Ọ̀jọ̀gbọ́n Obìnrin tí ọmọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà lórí Èdè àtí Ìbáraẹnisọ̀rọ̀, Ọ̀jọ̀gbọ́n Bolanle Akeredolu-Ale, ní wọ́n tí yàn gẹ́gẹ́bí Ìgbákejì àdarí ilé-ẹ̀kọ́ gíga tí ‘Pan African University’, tí Àjọ ‘African Union Commission’ ní Olú Ilé-iṣẹ́ wọ́n ní Yaoundé, Cameroon.
Ọ̀jọ̀gbọ́n Akeredolu-Ale jẹ́ gbajúgbajà lórí èdè àti Ìbáraẹnisọ̀rọ̀ ní Ilé-ìwé gíga tí ẹ̀kọ́ Àgbẹ̀ (Federal University of Agriculture FUNAAB), Abeokuta, , Ìpínlẹ̀ Ogun, Gúúsù ìwọ̀ oòrùn Nàìjíríà.
O tí ṣé ṣíṣẹ́ púpọ̀ sí ìdàgbàsókè tí ìròyìn ní Nàìjíríà àtí Áfíríkà nipasẹ ìkọ́ni àtí ìwádìí fún ọdún méjìlèl’ọgbọ̀n (32).
O tún jẹ́ ọmọ ẹgbẹ́ tí Iwadi Ẹkọ Ìròyìn, JETREG, láàrín àwọn mìíràn.