Gẹ́gẹ́ bí osù alápọ̀ńlé Ramadan Se ń súmọ́, ìjọba ìpínlẹ̀ Kano se àgbékalẹ̀ ìgbìmọ̀ tí yóò se ètò pínpín oúnjẹ nínú osù ààwẹ̀ náà
Olùfọ̀rọ̀léde fún igbákejì gómìnà ìpínlẹ̀ Kano, Ibrahim Garba Shuaibu sọ pé ìfilọ́lẹ̀ ìgbìmọ̀ náà wáyé láti pè fún ìsọ̀kan àti fún ìrànlọ́wọ́ ọmọnìyàn lásìkò ààwẹ̀
Ó sàfirinlẹ̀ pé ètò náà wáyé láti se ìrànlọ́wọ́ fún gbogbo olùgbé ìpínlẹ̀ kano láìfi ti ẹgbẹ́ òsèlú kankan se. Ó wá rọ ìgbìmọ̀ naa lati pín oúnjẹ na léyìí tí yóò kari gbogbo ara ilu.