Ààrẹ Bola Tinubu ti gúnlẹ̀ sí ìlú Eko láti Abuja fún pọ̀pọ̀-ṣìnṣìn ọdún pẹ̀lú èbì àti afeànifẹ́re rẹ̀.
Ààrẹ yóò dara pọ̀ mọ́ àwọn ẹlẹ́ṣìn ìgbàgbọ́ láti se ayẹyẹ ọdún kérésìmesì.
Ọkọ̀ òfurufú rẹ̀, Nigerian Air Force 001 balẹ̀ gùdẹ̀ sí pápákọ̀ Murtala Muhammad, abala ti ààrẹ ni dédé aago mẹ́rin ku ìṣẹ́jú marun-un ọ̀sán
Gómìnà ìpínlẹ̀ Èkó, Babajide Sanwo-Olu, àwọn jànkàn-jànkàn àti àwọn ọmọ ẹgbẹ́ òṣèlú All Progressives Congress party, APC ni wọ́n lọ pàdé rẹ̀.
Àwọn akọ́wọ́rìn pẹ̀lú ààrẹ doríkọ agbègbè Ìkòyí níbi ti ile ààrẹ wa yóò sì padà sí Aso Villa, ìlú Abuja lẹ́yìn ìsinmi lẹ́nu iṣẹ́.
Tèmítọ́pẹ́ Òbísẹ̀san