Ní wákàtí díẹ̀ sí àyájọ́ Ọdún iléyá, àwọn tí ó ń ta ẹran àgbò àti àwọn ọlọ́kọ̀ ti fi àìdùnnú ọkàn hàn látàrí àì-sí àwọn oníbàárà fún ọjà wọn ní ọdún yìí.
Àwọn olùwòye sọ wípé, kò sí àwọn oníbàárà ní ọjà ẹran ileya ni ipinlẹ Kano. Alhaji Yusuf Ahmed ti o jẹ alaga ọja Gidan Albasa tẹsiwaju pe, orisiirisii ẹran ileya ni o wa nínú ọjà bíi Àgbò, Ràkúnmí, Màálù sùgbọ́n ko si àwọn oníbàárà.
Ó sọ wípé, lóòtọ́ọ́ ni ọwọ ẹran gbowo lori, sùgbọ́n gẹgẹ bi àríwòye rẹ̀, owo ọkọ ati ounjẹ ẹran ti o gbowo lori ni o se okùnfà .
Leave a Reply