Lẹ́yìn idajọ láti ilé ẹjọ́ gíga tí Abuja tó kéde gomina Ademola Adeleke gẹ́gẹ́ bí ẹni tí ojawé olubori ni àwọn ọmọ ẹgbẹ́ òṣèlú PDP àti àwọn ará ìlú dawo ìdùnnú ni ile gomina tó wà ní country Home tó wà ní ìlú Ede ni Ipinlẹ Osun
Ilé ẹjọ́ ni ẹsùn tí wọ́n fi kan Gómìnà Ademola Adeleke nípa lílo ayédèrú ìwé ẹ̀rí kò fẹsè múlẹ̀

Ilé ẹjọ́ tún ní àwọn ẹlẹrìí tí ẹgbẹ́ òṣèlú APC ló nílé ẹjọ́ nípa pé wọ́n ṣe àlùkọ́rọ́yí ìbò (Over voting), kò yege láti jẹrìí.

Ilé ẹjọ́ tún faramo ìdájọ tí ilé ẹjọ kòtẹ́milọ́rùn dá, láti yí ohun ti ìgbìmọ̀ tó ń rí sí awuyewuye nípa ètò ìdìbò(election Tribunal) gómìnà ti wọ́n dá ní Òsogbo nù

Ní Ikaadi, Ilé ẹjọ́ ní àhesọ ọ̀rọ̀ ẹnu lásán ni pé,màgò-mágó wà nínú ìdìbò gómìnà tí wọ́n di.kò sí ẹ̀rí tó fìdí rẹ̀ múlẹ̀.
Leave a Reply