Take a fresh look at your lifestyle.

Ààrẹ Tinubu Tún Fi Ìdúróṣinṣin Rẹ̀ Múlẹ̀ Láti Fòpin Eí Iwà Ipá.

21

Ààrẹ Bola Ahmed Tinubu ti tún fi ìdúróṣinṣin ìjọba rẹ̀ hàn láti kojú ìwà ipá àti àwọn ìpèníjà ààbò mìíràn tó ń halẹ̀ mọ́ ìdúróṣinṣin  Orílẹ̀-èdè Nàìjíríà ó sì tún fi hàn wi pé orílẹ̀-èdè yìí yóò borí àwọn oniṣẹ ibi tó ń wá ọ̀nà láti ba àlàáfíà àti ìṣọ̀kan rẹ̀ jẹ́ nígbẹ̀yìn gbẹ́yín.

Ààrẹ fi  ìdánilójú naa hàn nígbà tó ń gbàlejò àwọn ọmọ ogun àti àwọn ilé iṣẹ́ ààbò mìíràn níbi ìfàájì ẹ̀sìn (ìfàájì ààwẹ̀) tí wọ́n ṣe ní Ilé Ìgbìmọ̀ ní Abuja.

 

Nígbà tó ń sọ̀rọ̀ lòdì sí ìkọlù àwọn oníjàǹbá láìpẹ́ yìí sí àwùjọ Ngoshe ní ìjọba ìbílẹ̀ Gwoza  ni Ìpínlẹ̀ Borno, Ààrẹ Tinubu fi ìgbẹ́kẹ̀lé hàn wi pé Orílẹ̀-èdè Nàìjíríà yóò borí àwọn ìpèníjà ààbò tó ń dojúkọ orílẹ̀-èdè yìí Lai pẹ.

Olórí ẹgbẹ́ ọmọ ologun tún fi ìmoore hàn sí àwọn ọmọ orílẹ̀-èdè Nàìjíríà fún atìlẹ́yìn wọn fún àwọn ọmọ ologun nínú ìjà tó ń lọ lọ́wọ́ lòdì sí àìní ààbò.

 

Comments are closed.

button